-
Jẹ́nẹ́sísì 47:29-31Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
29 Nígbà tí àkókò tí Ísírẹ́lì máa kú+ sún mọ́ tòsí, ó pe Jósẹ́fù ọmọ rẹ̀, ó sì sọ pé: “Tí mo bá rí ojúure rẹ, jọ̀ọ́ fi ọwọ́ rẹ sábẹ́ itan mi, kí o fi ìfẹ́ tí kì í yẹ̀ hàn sí mi, kí o sì jẹ́ olóòótọ́ sí mi. Jọ̀ọ́, má sin mí sí Íjíbítì.+ 30 Tí mo bá kú,* kí o gbé mi kúrò ní Íjíbítì, kí o sì lọ sin mí sí sàréè àwọn baba ńlá+ mi.” Jósẹ́fù fèsì pé: “Màá ṣe ohun tí o sọ.” 31 Ísírẹ́lì wá sọ pé: “Búra fún mi.” Ó sì búra fún un.+ Ísírẹ́lì sì tẹrí ba níbi ìgbèrí ibùsùn+ rẹ̀.
-