3 Àmọ́ ẹ̀rù ń bà mí pé lọ́nà kan ṣáá, bí ejò ṣe fi ẹ̀tàn fa ojú Éfà mọ́ra,+ a lè sọ ìrònú yín dìbàjẹ́, tí ẹ ó sì yà kúrò nínú òtítọ́ inú àti ìwà mímọ́* tó yẹ Kristi.+
9 A wá ju dírágónì ńlá+ náà sísàlẹ̀, ejò àtijọ́ náà,+ ẹni tí à ń pè ní Èṣù+ àti Sátánì,+ tó ń ṣi gbogbo ilẹ̀ ayé tí à ń gbé lọ́nà;+ a jù ú sí ayé,+ a sì ju àwọn áńgẹ́lì rẹ̀ sísàlẹ̀ pẹ̀lú rẹ̀.