-
Ẹ́kísódù 28:31-35Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
31 “Fọ́nrán òwú aláwọ̀ búlúù ni kí o lò látòkè délẹ̀ láti fi ṣe aṣọ àwọ̀lékè tí kò lápá sí éfódì náà.+ 32 Kí o yọ ọrùn* sí aṣọ náà, ní àárín. Kí ẹni tó ń hun aṣọ ṣe ìgbátí sí ọrùn rẹ̀ yí ká. Kí o ṣe ọrùn aṣọ náà bíi ti ẹ̀wù irin, kó má bàa ya. 33 Kí o fi fọ́nrán òwú aláwọ̀ búlúù, òwú aláwọ̀ pọ́pù àti òwú aláwọ̀ rírẹ̀dòdò ṣe pómégíránétì sí etí aṣọ náà yí ká, kí o sì fi àwọn agogo wúrà sáàárín wọn. 34 Kí o to agogo wúrà kan tẹ̀ lé pómégíránétì kan, agogo wúrà kan tẹ̀ lé pómégíránétì kan yí ká etí aṣọ àwọ̀lékè tí kò lápá náà. 35 Kí Áárónì wọ̀ ọ́ kó lè máa fi ṣiṣẹ́, kí àwọn ohun tó wà lára aṣọ náà sì máa dún nígbà tó bá ń wọ inú ibi mímọ́ níwájú Jèhófà àti nígbà tó bá ń jáde, kó má bàa kú.+
-