21 Orílẹ̀-èdè wo ní gbogbo ayé ló dà bí àwọn èèyàn rẹ Ísírẹ́lì?+ Ọlọ́run tòótọ́ lọ rà wọ́n pa dà nítorí wọ́n jẹ́ èèyàn rẹ̀.+ O ṣe orúkọ fún ara rẹ bí o ṣe ń ṣe àwọn ohun ńlá àti àwọn ohun àgbàyanu,+ tí o sì ń lé àwọn orílẹ̀-èdè kúrò níwájú àwọn èèyàn rẹ+ tí o rà pa dà láti Íjíbítì.
17 Ọlọ́run àwọn èèyàn Ísírẹ́lì yìí yan àwọn baba ńlá wa, ó gbé àwọn èèyàn náà ga nígbà tí wọ́n jẹ́ àjèjì ní ilẹ̀ Íjíbítì, ó sì fi ọwọ́ agbára* mú wọn jáde kúrò níbẹ̀.+