- 
	                        
            
            Ẹ́kísódù 8:7Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
- 
                            - 
                                        7 Àmọ́ àwọn àlùfáà onídán fi agbára òkùnkùn wọn ṣe ohun kan náà, àwọn náà mú kí àkèré jáde sórí ilẹ̀ Íjíbítì.+ 
 
- 
                                        
- 
	                        
            
            Ẹ́kísódù 8:18Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
- 
                            - 
                                        18 Àwọn àlùfáà onídán náà gbìyànjú láti ṣe ohun kan náà, wọ́n fẹ́ fi agbára òkùnkùn wọn mú kòkòrò jáde,+ àmọ́ wọn ò rí i ṣe. Àwọn kòkòrò náà bo èèyàn àti ẹranko. 
 
- 
                                        
- 
	                        
            
            Ẹ́kísódù 9:11Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
- 
                            - 
                                        11 Àwọn àlùfáà onídán kò lè dúró níwájú Mósè torí eéwo náà, torí eéwo ti bo àwọn àlùfáà náà àti gbogbo ará Íjíbítì.+ 
 
- 
                                        
- 
	                        
            
            2 Tímótì 3:8Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
- 
                            - 
                                        8 Bí Jánésì àti Jáńbérì ṣe ta ko Mósè, bẹ́ẹ̀ náà ni àwọn yìí ṣe ń ta ko òtítọ́ ṣáá. Ìrònú irú àwọn èèyàn bẹ́ẹ̀ ti dìbàjẹ́, ìgbàgbọ́ wọn ò sì ní ìtẹ́wọ́gbà. 
 
-