3 O ò gbọ́dọ̀ jẹ ohunkóhun tó ní ìwúkàrà pẹ̀lú rẹ̀;+ ọjọ́ méje ni kí o fi jẹ búrẹ́dì aláìwú, ó jẹ́ oúnjẹ ìpọ́njú, torí pé ẹ kánjú kúrò ní ilẹ̀ Íjíbítì.+ Máa ṣe èyí ní gbogbo ìgbà tí o bá fi wà láàyè kí o lè máa rántí ọjọ́ tí o kúrò ní ilẹ̀ Íjíbítì.+
7 Ẹ mú ìwúkàrà àtijọ́ kúrò, kí ẹ lè di ìṣùpọ̀ tuntun, tí kò bá ti sí amóhunwú nínú yín. Torí, ní tòótọ́, a ti fi Kristi ọ̀dọ́ àgùntàn Ìrékọjá wa+ rúbọ.+