42 Òru yẹn ni wọ́n á ṣe àjọyọ̀ torí pé Jèhófà mú wọn kúrò ní ilẹ̀ Íjíbítì. Kí gbogbo ọmọ Ísírẹ́lì máa pa òru ọjọ́ yìí mọ́ jálẹ̀ àwọn ìran wọn láti bọlá fún Jèhófà.+
3 O ò gbọ́dọ̀ jẹ ohunkóhun tó ní ìwúkàrà pẹ̀lú rẹ̀;+ ọjọ́ méje ni kí o fi jẹ búrẹ́dì aláìwú, ó jẹ́ oúnjẹ ìpọ́njú, torí pé ẹ kánjú kúrò ní ilẹ̀ Íjíbítì.+ Máa ṣe èyí ní gbogbo ìgbà tí o bá fi wà láàyè kí o lè máa rántí ọjọ́ tí o kúrò ní ilẹ̀ Íjíbítì.+