21 Ní ọ̀sán, Jèhófà máa ń lọ níwájú wọn nínú ọwọ̀n ìkùukùu* kó lè máa darí wọn lójú ọ̀nà,+ àmọ́ ní òru, ó máa ń lọ níwájú wọn nínú ọwọ̀n iná* kó lè fún wọn ní ìmọ́lẹ̀, kí wọ́n lè máa bá ìrìn àjò wọn lọ tọ̀sántòru.+
5 Bí wọ́n ṣe ń sọ̀rọ̀ lọ́wọ́, wò ó! ìkùukùu* tó mọ́lẹ̀ yòò ṣíji bò wọ́n, sì wò ó! ohùn kan dún látinú ìkùukùu náà pé: “Èyí ni Ọmọ mi, àyànfẹ́, ẹni tí mo ti tẹ́wọ́ gbà.+ Ẹ fetí sí i.”+