-
Ẹ́kísódù 29:22-25Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
22 “Kí o yọ ọ̀rá lára àgbò náà, kí o gé ìrù rẹ̀ tó lọ́ràá, ọ̀rá tó bo ìfun, àmọ́ tó wà lára ẹ̀dọ̀, kíndìnrín méjèèjì àti ọ̀rá tó wà lára wọn,+ pẹ̀lú ẹsẹ̀ rẹ̀ ọ̀tún, torí ó jẹ́ àgbò àfiyanni.+ 23 Kí o tún mú búrẹ́dì ribiti kan àti búrẹ́dì tí wọ́n fi òróró sí tó rí bí òrùka àti búrẹ́dì pẹlẹbẹ kan látinú apẹ̀rẹ̀ búrẹ́dì aláìwú tó wà níwájú Jèhófà. 24 Kí o kó gbogbo wọn sí ọwọ́ Áárónì àti sí ọwọ́ àwọn ọmọ rẹ̀, kí o sì fì wọ́n síwá-sẹ́yìn bí ọrẹ fífì níwájú Jèhófà. 25 Kí o wá gbà á lọ́wọ́ wọn, kí o sì sun ún lórí pẹpẹ, lórí ẹbọ sísun, kó lè mú òórùn dídùn* jáde níwájú Jèhófà. Ọrẹ àfinásun sí Jèhófà ló jẹ́.
-