ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Léfítíkù 16:5
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 5 “Kó mú òbúkọ méjì tó ṣì kéré látinú àpéjọ àwọn ọmọ Ísírẹ́lì+ láti fi rú ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀, kó sì fi àgbò kan rú ẹbọ sísun.

  • Hébérù 2:17
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 17 Bákan náà, ó ní láti dà bí “àwọn arákùnrin” rẹ̀ ní gbogbo ọ̀nà,+ kó lè di àlùfáà àgbà tó jẹ́ aláàánú àti olóòótọ́ nínú àwọn ohun tó jẹ mọ́ ti Ọlọ́run, kó lè rú ẹbọ ìpẹ̀tù*+ fún ẹ̀ṣẹ̀ àwọn èèyàn.+

  • Hébérù 5:1-3
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 5 Torí gbogbo àlùfáà àgbà tí a mú láàárín àwọn èèyàn ni a yàn nítorí wọn láti bójú tó àwọn ohun tó jẹ mọ́ Ọlọ́run,+ kó lè fi àwọn ọrẹ àti ẹbọ rúbọ nítorí ẹ̀ṣẹ̀.+ 2 Ó ṣeé ṣe fún un láti ṣàánú àwọn aláìmọ̀kan* àti àwọn tó ń ṣàṣìṣe,* torí òun náà ní àìlera tiẹ̀,* 3 ìdí nìyẹn tí òun náà fi gbọ́dọ̀ rú ẹbọ nítorí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ tiẹ̀, bó ṣe ń ṣe nítorí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn èèyàn gẹ́lẹ́.+

  • Hébérù 9:26
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 26 Àìjẹ́ bẹ́ẹ̀, ì bá máa jìyà léraléra látìgbà ìpìlẹ̀ ayé. Àmọ́ ní báyìí, ó ti fi ara rẹ̀ hàn kedere ní ìparí àwọn ètò àwọn nǹkan,* lẹ́ẹ̀kan ṣoṣo láìtún ní ṣe é mọ́ láé, ó fi ara rẹ̀ rúbọ kó lè mú ẹ̀ṣẹ̀ kúrò.+

  • 1 Jòhánù 2:1, 2
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 2 Ẹ̀yin ọmọ mi kéékèèké, mò ń kọ àwọn nǹkan yìí sí yín kí ẹ má bàa dẹ́ṣẹ̀. Síbẹ̀, tí ẹnikẹ́ni bá dẹ́ṣẹ̀, a ní olùrànlọ́wọ́* lọ́dọ̀ Baba, Jésù Kristi,+ ẹni tó jẹ́ olódodo.+ 2 Òun sì ni ẹbọ ìpẹ̀tù*+ fún àwọn ẹ̀ṣẹ̀ wa,+ síbẹ̀ kì í ṣe fún ẹ̀ṣẹ̀ tiwa nìkan, àmọ́ fún gbogbo ayé pẹ̀lú.+

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́