Diutarónómì 15:7 Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun 7 “Tí ọ̀kan lára àwọn arákùnrin rẹ bá di aláìní láàárín rẹ nínú ọ̀kan lára àwọn ìlú rẹ ní ilẹ̀ tí Jèhófà Ọlọ́run rẹ fẹ́ fún ọ, o ò gbọ́dọ̀ mú kí ọkàn rẹ le tàbí kí o háwọ́ sí arákùnrin rẹ tó jẹ́ aláìní.+ Sáàmù 41:1 Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun 41 Aláyọ̀ ni ẹni tó bá ń ro ti àwọn aláìní;+Jèhófà yóò gbà á sílẹ̀ ní ọjọ́ àjálù. Sáàmù 112:5 Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun 5 Nǹkan máa ń lọ dáadáa fún ẹni tó bá ń yáni ní nǹkan tọkàntọkàn.*+ י [Yódì] Ìdájọ́ òdodo ló fi ń ṣe nǹkan. Òwe 3:27 Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun 27 Má fawọ́ ohun rere sẹ́yìn kúrò lọ́dọ̀ àwọn tó yẹ kí o ṣe é fún*+Tó bá wà níkàáwọ́ rẹ* láti ṣe é.+ Òwe 19:17 Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun 17 Ẹni tó ń ṣojúure sí aláìní, Jèhófà ló ń yá ní nǹkan,+Á sì san án* pa dà fún un nítorí ohun tó ṣe.+ Máàkù 14:7 Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun 7 Torí ìgbà gbogbo ni àwọn aláìní wà láàárín yín,+ ẹ sì lè ṣe ohun rere sí wọn nígbàkigbà tí ẹ bá fẹ́, àmọ́ ìgbà gbogbo kọ́ ni màá wà láàárín yín.+ Ìṣe 11:29 Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun 29 Torí náà, àwọn ọmọ ẹ̀yìn pinnu, gẹ́gẹ́ bí ohun tí agbára kálukú wọn gbé,+ láti fi nǹkan ìrànwọ́*+ ránṣẹ́ sí àwọn ará tó ń gbé ní Jùdíà; 1 Tímótì 6:18 Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun 18 Sọ fún wọn pé kí wọ́n máa ṣe rere, àní kí wọ́n máa ṣe ọ̀pọ̀lọpọ̀ iṣẹ́ rere, kí wọ́n jẹ́ ọ̀làwọ́,* kí wọ́n ṣe tán láti máa fúnni,+ 1 Jòhánù 3:17 Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun 17 Àmọ́ ẹnikẹ́ni tó bá ní ohun ìní ayé yìí, tó sì rí i pé arákùnrin rẹ̀ ṣaláìní síbẹ̀ tí kò ṣàánú rẹ̀, báwo ni ìfẹ́ Ọlọ́run ṣe wà nínú rẹ̀?+
7 “Tí ọ̀kan lára àwọn arákùnrin rẹ bá di aláìní láàárín rẹ nínú ọ̀kan lára àwọn ìlú rẹ ní ilẹ̀ tí Jèhófà Ọlọ́run rẹ fẹ́ fún ọ, o ò gbọ́dọ̀ mú kí ọkàn rẹ le tàbí kí o háwọ́ sí arákùnrin rẹ tó jẹ́ aláìní.+
5 Nǹkan máa ń lọ dáadáa fún ẹni tó bá ń yáni ní nǹkan tọkàntọkàn.*+ י [Yódì] Ìdájọ́ òdodo ló fi ń ṣe nǹkan.
17 Ẹni tó ń ṣojúure sí aláìní, Jèhófà ló ń yá ní nǹkan,+Á sì san án* pa dà fún un nítorí ohun tó ṣe.+
7 Torí ìgbà gbogbo ni àwọn aláìní wà láàárín yín,+ ẹ sì lè ṣe ohun rere sí wọn nígbàkigbà tí ẹ bá fẹ́, àmọ́ ìgbà gbogbo kọ́ ni màá wà láàárín yín.+
29 Torí náà, àwọn ọmọ ẹ̀yìn pinnu, gẹ́gẹ́ bí ohun tí agbára kálukú wọn gbé,+ láti fi nǹkan ìrànwọ́*+ ránṣẹ́ sí àwọn ará tó ń gbé ní Jùdíà;
18 Sọ fún wọn pé kí wọ́n máa ṣe rere, àní kí wọ́n máa ṣe ọ̀pọ̀lọpọ̀ iṣẹ́ rere, kí wọ́n jẹ́ ọ̀làwọ́,* kí wọ́n ṣe tán láti máa fúnni,+
17 Àmọ́ ẹnikẹ́ni tó bá ní ohun ìní ayé yìí, tó sì rí i pé arákùnrin rẹ̀ ṣaláìní síbẹ̀ tí kò ṣàánú rẹ̀, báwo ni ìfẹ́ Ọlọ́run ṣe wà nínú rẹ̀?+