-
Ẹ́kísódù 32:27Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
27 Ó wá sọ fún wọn pé: “Ohun tí Jèhófà Ọlọ́run Ísírẹ́lì sọ nìyí, ‘Kí kálukú yín sán idà rẹ̀ mọ́ ẹ̀gbẹ́, kí ẹ sì lọ káàkiri àgọ́ náà láti ẹnubodè sí ẹnubodè, kí kálukú pa arákùnrin rẹ̀, aládùúgbò rẹ̀ àti ọ̀rẹ́ rẹ̀ tímọ́tímọ́.’”+
-
-
Léfítíkù 10:6, 7Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
6 Mósè wá sọ fún Áárónì àti àwọn ọmọ rẹ̀ yòókù, Élíásárì àti Ítámárì, pé: “Ẹ má fi irun orí yín sílẹ̀ láìtọ́jú, ẹ ò sì gbọ́dọ̀ ya aṣọ yín,+ kí ẹ má bàa kú, kí Ọlọ́run má bàa bínú sí gbogbo àpéjọ yìí. Àwọn arákùnrin yín ní gbogbo ilé Ísírẹ́lì máa sunkún torí àwọn tí Jèhófà fi iná pa. 7 Ẹ ò gbọ́dọ̀ jáde ní ẹnu ọ̀nà àgọ́ ìpàdé, àìjẹ́ bẹ́ẹ̀, ẹ máa kú, torí òróró àfiyanni Jèhófà wà lórí yín.”+ Torí náà, wọ́n ṣe ohun tí Mósè sọ.
-