-
Nọ́ńbà 32:1-5Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
32 Ó ṣẹlẹ̀ pé àwọn ọmọ Rúbẹ́nì+ àti àwọn ọmọ Gádì+ ní ẹran ọ̀sìn tó pọ̀ gan-an, wọ́n sì rí i pé ilẹ̀ Jásérì+ àti ilẹ̀ Gílíádì dáa fún àwọn ẹran ọ̀sìn. 2 Torí náà, àwọn ọmọ Gádì àti àwọn ọmọ Rúbẹ́nì lọ bá Mósè àti àlùfáà Élíásárì pẹ̀lú àwọn ìjòyè àpéjọ náà pé: 3 “Átárótì, Díbónì, Jásérì, Nímírà, Hẹ́ṣíbónì,+ Éléálè, Sébámù, Nébò+ àti Béónì,+ 4 àwọn ilẹ̀ tí Jèhófà bá àpéjọ àwọn ọmọ Ísírẹ́lì+ ṣẹ́gun, dáa fún àwọn ẹran ọ̀sìn,+ ẹran ọ̀sìn àwa ìránṣẹ́ rẹ sì pọ̀ gan-an.” 5 Wọ́n ń bá ọ̀rọ̀ wọn lọ pé: “Tí a bá rí ojúure rẹ, jẹ́ kí ilẹ̀ yìí di ohun ìní àwa ìránṣẹ́ rẹ. Má ṣe jẹ́ ká sọdá Jọ́dánì.”
-