11 Gbogbo ohun tí mò ń pa láṣẹ fún yín ni kí ẹ mú wá sí ibi tí Jèhófà Ọlọ́run yín yàn pé kí orúkọ rẹ̀ máa wà,+ ìyẹn àwọn ẹbọ sísun yín, àwọn ẹbọ yín, àwọn ìdá mẹ́wàá yín,+ ọrẹ látọwọ́ yín àti gbogbo ọrẹ tí ẹ jẹ́jẹ̀ẹ́ fún Jèhófà.
12 “Tí o bá ti kó gbogbo ìdá mẹ́wàá+ èso ilẹ̀ rẹ jọ tán ní ọdún kẹta, ọdún ìdá mẹ́wàá, kí o fún ọmọ Léfì, àjèjì, ọmọ aláìníbaba* àti opó, kí wọ́n sì jẹ ẹ́ yó nínú àwọn ìlú* rẹ.+