ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Jẹ́nẹ́sísì 15:18
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 18 Ní ọjọ́ yẹn, Jèhófà bá Ábúrámù dá májẹ̀mú+ kan pé: “Ọmọ* rẹ ni èmi yóò fún ní ilẹ̀ yìí,+ láti odò Íjíbítì dé odò ńlá náà, ìyẹn odò Yúfírétì:+

  • Ẹ́kísódù 23:31
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 31 “Màá pààlà fún yín láti Òkun Pupa dé òkun àwọn Filísínì àti láti aginjù dé Odò;*+ torí màá mú kí ọwọ́ yín tẹ àwọn tó ń gbé ilẹ̀ náà, ẹ ó sì lé wọn kúrò níwájú yín.+

  • Nọ́ńbà 34:2, 3
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 2 “Fi ìtọ́ni yìí tó àwọn ọmọ Ísírẹ́lì létí pé, ‘Tí ẹ bá wọ ilẹ̀ Kénáánì,+ ilẹ̀ tó máa di tiyín nìyí láwọn ibi tí ààlà+ rẹ̀ dé.

      3 “‘Kí ààlà gúúsù yín bẹ̀rẹ̀ láti aginjù Síínì lẹ́gbẹ̀ẹ́ Édómù, kí ààlà gúúsù yín lápá ìlà oòrùn sì jẹ́ láti ìkángun Òkun Iyọ̀.*+

  • Diutarónómì 1:7
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 7 Ẹ ṣẹ́rí pa dà, kí ẹ sì máa lọ sí agbègbè olókè àwọn Ámórì,+ kí ẹ forí lé ọ̀dọ̀ gbogbo àwọn tó yí wọn ká ní Árábà,+ agbègbè olókè, Ṣẹ́fẹ́là, Négébù àti etí òkun,  + ilẹ̀ àwọn ọmọ Kénáánì àti Lẹ́bánónì,*+ títí dé odò ńlá, ìyẹn odò Yúfírétì.+

  • Jóṣúà 15:1
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 15 Ilẹ̀ tí wọ́n pín+ fún ẹ̀yà Júdà ní ìdílé-ìdílé lọ dé ààlà Édómù,+ aginjù Síínì, dé ìpẹ̀kun Négébù lápá gúúsù.

  • Jóṣúà 15:4
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 4 Ó tún lọ dé Ásímónì,+ títí dé Àfonífojì Íjíbítì,+ ààlà náà sì parí sí Òkun.* Èyí ni ààlà wọn lápá gúúsù.

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́