ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • 1 Àwọn Ọba 5:3
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 3 “O mọ̀ dáadáa pé Dáfídì bàbá mi kò lè kọ́ ilé fún orúkọ Jèhófà Ọlọ́run rẹ̀ nítorí ogun tí wọ́n fi yí i ká, títí Jèhófà fi fi àwọn ọ̀tá rẹ̀ sábẹ́ àtẹ́lẹsẹ̀ rẹ̀.+

  • 1 Àwọn Ọba 8:17-19
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 17 Ó jẹ́ ìfẹ́ ọkàn Dáfídì bàbá mi pé kí ó kọ́ ilé fún orúkọ Jèhófà Ọlọ́run Ísírẹ́lì.+ 18 Ṣùgbọ́n Jèhófà sọ fún Dáfídì bàbá mi pé, ‘Ìfẹ́ ọkàn rẹ ni pé kí o kọ́ ilé fún orúkọ mi, ó sì dára bó ṣe ń wù ọ́ yìí. 19 Àmọ́, ìwọ kọ́ ló máa kọ́ ilé náà, ọmọ tí o máa bí* ló máa kọ́ ilé fún orúkọ mi.’+

  • 1 Kíróníkà 17:4-6
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 4 “Lọ sọ fún Dáfídì ìránṣẹ́ mi pé, ‘Ohun tí Jèhófà sọ nìyí: “Ìwọ kọ́ ló máa kọ́ ilé tí màá gbé fún mi.+ 5 Nítorí mi ò gbé inú ilé láti ọjọ́ tí mo ti mú Ísírẹ́lì jáde títí di òní yìí, àmọ́ mò ń lọ láti àgọ́ dé àgọ́ àti látinú àgọ́ ìjọsìn kan dé òmíràn.*+ 6 Ní gbogbo àkókò tí mò ń bá gbogbo Ísírẹ́lì rìn, ṣé mo fìgbà kankan sọ fún ọ̀kan lára àwọn onídàájọ́ tí mo yàn láti máa bójú tó àwọn èèyàn mi Ísírẹ́lì bí àgùntàn, pé, ‘Kí ló dé tí ẹ ò fi kọ́ ilé onígi kédárì fún mi?’”’

  • 1 Kíróníkà 22:7, 8
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 7 Dáfídì sọ fún Sólómọ́nì ọmọ rẹ̀ pé: “Ní tèmi, ìfẹ́ ọkàn mi ni láti kọ́ ilé fún orúkọ Jèhófà Ọlọ́run mi.+ 8 Àmọ́ Jèhófà bá mi sọ̀rọ̀, ó ní, ‘O ti ta ẹ̀jẹ̀ tó pọ̀ gan-an sílẹ̀, o sì ti ja àwọn ogun ńlá. O ò ní kọ́ ilé fún orúkọ mi,+ nítorí o ti ta ẹ̀jẹ̀ tó pọ̀ gan-an sílẹ̀ níwájú mi.

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́