-
2 Sámúẹ́lì 4:5-8Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
5 Àwọn ọmọ Rímónì ará Béérótì, ìyẹn Rékábù àti Báánà, lọ sí ilé Íṣí-bóṣétì ní ọ̀sán gangan, nígbà tí ó ń sun oorun ọ̀sán lọ́wọ́. 6 Wọ́n wọnú ilé náà bíi pé wọ́n fẹ́ wá kó àlìkámà,* wọ́n sì gún un ní ikùn; Rékábù àti Báánà+ arákùnrin rẹ̀ sì sá lọ. 7 Nígbà tí wọ́n wọnú ilé, ó ń sùn lórí ibùsùn nínú yàrá rẹ̀, wọ́n gún un pa, wọ́n sì gé orí rẹ̀ kúrò. Wọ́n gbé orí rẹ̀, wọ́n sì gba ọ̀nà tó lọ sí Árábà láti òru mọ́jú. 8 Wọ́n gbé orí Íṣí-bóṣétì + wá fún Dáfídì ní Hébúrónì, wọ́n sì sọ fún ọba pé: “Orí Íṣí-bóṣétì ọmọ Sọ́ọ̀lù ọ̀tá rẹ+ tí ó fẹ́ gba ẹ̀mí* rẹ+ rèé. Jèhófà ti bá olúwa mi ọba gbẹ̀san lára Sọ́ọ̀lù àti àwọn ọmọ rẹ̀ lónìí yìí.”
-