-
2 Sámúẹ́lì 9:7-10Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
7 Dáfídì sọ fún un pé: “Má bẹ̀rù, màá rí i dájú pé mo fi ìfẹ́ tí kì í yẹ̀+ hàn sí ọ nítorí Jónátánì bàbá rẹ, màá dá gbogbo ilẹ̀ Sọ́ọ̀lù bàbá rẹ àgbà pa dà fún ọ, orí tábìlì mi + ni wàá sì ti máa jẹun* nígbà gbogbo.”
8 Ni ó bá wólẹ̀, ó sì sọ pé: “Kí ni èmi ìránṣẹ́ rẹ já mọ́, tí o fi yí ojú* rẹ sí òkú ajá+ bíi tèmi?” 9 Ọba wá ránṣẹ́ pe Síbà, ẹmẹ̀wà* Sọ́ọ̀lù, ó sì sọ fún un pé: “Gbogbo ohun tí Sọ́ọ̀lù àti gbogbo ilé rẹ̀ ní ni mo fún ọmọ ọmọ ọ̀gá rẹ.+ 10 Ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ ni á máa bá a dá oko, wàá máa kó irè oko jọ láti pèsè oúnjẹ tí àwọn ará ilé ọmọ ọmọ ọ̀gá rẹ á máa jẹ. Àmọ́ orí tábìlì mi+ ni Méfíbóṣétì, ọmọ ọmọ ọ̀gá rẹ, á ti máa jẹun nígbà gbogbo.”
Síbà ní ọmọkùnrin mẹ́ẹ̀ẹ́dógún (15) àti ogún (20) ìránṣẹ́.+
-