-
1 Kíróníkà 21:18-23Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
18 Lẹ́yìn náà, áńgẹ́lì Jèhófà ní kí Gádì+ sọ fún Dáfídì pé kó lọ ṣé pẹpẹ kan fún Jèhófà ní ibi ìpakà Ọ́nánì ará Jébúsì.+ 19 Torí náà, Dáfídì lọ ṣe ohun tí Gádì sọ, èyí tó sọ fún un ní orúkọ Jèhófà. 20 Lákòókò yìí, Ọ́nánì bojú wẹ̀yìn, ó rí áńgẹ́lì náà, àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ mẹ́rẹ̀ẹ̀rin tó wà lọ́dọ̀ rẹ̀ sì fara pa mọ́. Nígbà yẹn, Ọ́nánì ń pa ọkà àlìkámà.* 21 Nígbà tí Dáfídì dé ọ̀dọ̀ Ọ́nánì, Ọ́nánì gbójú sókè, ó sì rí Dáfídì, lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀, ó kúrò ní ibi ìpakà náà, ó tẹrí ba fún Dáfídì, ó sì dojú bolẹ̀. 22 Dáfídì sọ fún Ọ́nánì pé: “Ta* ilẹ̀ tó wá ní ibi ìpakà yìí fún mi, kí n lè mọ pẹpẹ kan síbẹ̀ fún Jèhófà. Iye tó bá jẹ́ ni kí o tà á fún mi, kí àjàkálẹ̀ àrùn tó ń pa àwọn èèyàn yìí lè dáwọ́ dúró.”+ 23 Ṣùgbọ́n Ọ́nánì sọ fún Dáfídì pé: “Máa mú un, kí olúwa mi ọba ṣe ohun tó bá rí pé ó dára.* Mo tún fi màlúù sílẹ̀ fún àwọn ẹbọ sísun àti ohun èlò ìpakà+ láti fi ṣe igi ìdáná àti àlìkámà* fún ọrẹ ọkà. Gbogbo rẹ̀ ni mo fi sílẹ̀.”
-