-
2 Kíróníkà 6:3-11Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
3 Lẹ́yìn náà, ọba yíjú pa dà, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í súre fún gbogbo ìjọ Ísírẹ́lì, bí gbogbo ìjọ Ísírẹ́lì ṣe wà ní ìdúró.+ 4 Ó sọ pé: “Ìyìn ni fún Jèhófà Ọlọ́run Ísírẹ́lì, ẹni tó fi ẹnu ara rẹ̀ ṣèlérí fún Dáfídì bàbá mi, tó sì fi ọwọ́ ara rẹ̀ mú un ṣẹ, tó sọ pé, 5 ‘Láti ọjọ́ tí mo ti mú àwọn èèyàn mi jáde kúrò ní ilẹ̀ Íjíbítì, mi ò yan ìlú kankan nínú gbogbo ẹ̀yà Ísírẹ́lì tí màá kọ́ ilé sí fún orúkọ mi, kí ó lè máa wà níbẹ̀,+ mi ò sì yan ọkùnrin kankan láti jẹ́ aṣáájú lórí àwọn èèyàn mi Ísírẹ́lì. 6 Ṣùgbọ́n mo ti yan Jerúsálẹ́mù+ kí orúkọ mi lè máa wà níbẹ̀, mo sì ti yan Dáfídì láti ṣe olórí àwọn èèyàn mi Ísírẹ́lì.’+ 7 Ó jẹ́ ìfẹ́ ọkàn Dáfídì bàbá mi pé kí ó kọ́ ilé fún orúkọ Jèhófà Ọlọ́run Ísírẹ́lì.+ 8 Àmọ́, Jèhófà sọ fún Dáfídì bàbá mi pé, ‘Ìfẹ́ ọkàn rẹ ni pé kí o kọ́ ilé fún orúkọ mi, ó sì dára bó ṣe ń wù ọ́ yìí. 9 Ṣùgbọ́n, ìwọ kọ́ ló máa kọ́ ilé náà, ọmọ tí o máa bí* ló máa kọ́ ilé fún orúkọ mi.’+ 10 Jèhófà ti mú ìlérí rẹ̀ ṣẹ, torí mo ti jọba ní ipò Dáfídì bàbá mi, mo sì jókòó lórí ìtẹ́ Ísírẹ́lì,+ bí Jèhófà ti ṣèlérí.+ Mo tún kọ́ ilé kan fún orúkọ Jèhófà Ọlọ́run Ísírẹ́lì, 11 ibẹ̀ ni mo sì gbé Àpótí tí májẹ̀mú+ Jèhófà wà nínú rẹ̀ sí, èyí tó bá àwọn ọmọ Ísírẹ́lì dá.”
-