-
2 Kíróníkà 10:8-11Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
8 Àmọ́, ó kọ ìmọ̀ràn tí àwọn àgbà ọkùnrin* fún un, ó sì fọ̀rọ̀ lọ àwọn ọ̀dọ́kùnrin tí wọ́n jọ dàgbà, àmọ́ tí wọ́n ti di ẹmẹ̀wà* rẹ̀ báyìí.+ 9 Ó béèrè lọ́wọ́ wọn pé: “Ẹ gbà mí nímọ̀ràn, èsì wo ni ká fún àwọn èèyàn tó sọ fún mi pé, ‘Mú kí àjàgà tí bàbá rẹ fi kọ́ wa lọ́rùn fúyẹ́’?” 10 Àwọn ọ̀dọ́kùnrin tí wọ́n jọ dàgbà sọ fún un pé: “Èyí ni ohun tí o máa sọ fún àwọn èèyàn tó sọ fún ọ pé, ‘Bàbá rẹ mú kí àjàgà wa wúwo, ṣùgbọ́n mú kí ó fúyẹ́ lọ́rùn wa’; ohun tí wàá sọ fún wọn ni pé, ‘Ọmọ ìka ọwọ́ mi tó kéré jù* yóò nípọn ju ìbàdí bàbá mi lọ. 11 Bàbá mi fi àjàgà tó wúwo kọ́ yín lọ́rùn, àmọ́ ńṣe ni màá fi kún àjàgà yín. Pàṣán ni bàbá mi fi nà yín, ṣùgbọ́n kòbókò oníkókó ni màá fi nà yín.’”
-