19 Tí wọ́n bá sì sọ fún yín pé: “Ẹ lọ wádìí lọ́wọ́ àwọn abẹ́mìílò tàbí àwọn woṣẹ́woṣẹ́, àwọn tó ń ké ṣíoṣío, tí wọ́n sì ń jẹnu wúyẹ́wúyẹ́,” ṣebí ọwọ́ Ọlọ́run wọn ló yẹ kí àwọn èèyàn ti lọ wádìí? Ṣé ó yẹ kí wọ́n lọ wádìí ọ̀rọ̀ lọ́wọ́ òkú nítorí alààyè?+