-
2 Àwọn Ọba 21:7-9Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
7 Ó gbé ère òpó òrìṣà*+ tó gbẹ́ wá sínú ilé tí Jèhófà sọ nípa rẹ̀ fún Dáfídì àti Sólómọ́nì ọmọ rẹ̀ pé: “Inú ilé yìí àti ní Jerúsálẹ́mù, tí mo ti yàn nínú gbogbo ẹ̀yà Ísírẹ́lì, ni màá fi orúkọ mi sí títí láé.+ 8 Mi ò tún ní mú kí Ísírẹ́lì rìn gbéregbère kúrò ní ilẹ̀ tí mo fún àwọn baba ńlá wọn,+ tí wọ́n bá ṣáà ti rí i pé wọ́n tẹ̀ lé gbogbo ohun tí mo pa láṣẹ fún wọn,+ ìyẹn gbogbo Òfin tí Mósè ìránṣẹ́ mi pa láṣẹ fún wọn pé kí wọ́n máa tẹ̀ lé.” 9 Àmọ́, wọn kò ṣègbọràn, Mánásè sì ń ṣì wọ́n lọ́nà, ó ń mú kí wọ́n ṣe ohun tó burú ju ti àwọn orílẹ̀-èdè tí Jèhófà pa run kúrò níwájú àwọn ọmọ Ísírẹ́lì.+
-