36 Ẹni ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n (25) ni Jèhóákímù+ nígbà tó jọba, ọdún mọ́kànlá (11) ló sì fi ṣàkóso ní Jerúsálẹ́mù.+ Orúkọ ìyá rẹ̀ ni Sébídà ọmọ Pedáyà láti Rúmà. 37 Ó ń ṣe ohun tó burú ní ojú Jèhófà,+ gbogbo ohun tí àwọn bàbá ńlá rẹ̀ ṣe ni òun náà ṣe.+