-
2 Kíróníkà 13:12Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
12 Ẹ wò ó! Ọlọ́run tòótọ́ wà pẹ̀lú wa, ó ń darí wa. Àwọn àlùfáà rẹ̀ sì wà níbí láti máa fun kàkàkí láti fi pe ogun sí yín. Ẹ̀yin ọmọ Ísírẹ́lì, ẹ má ṣe bá Jèhófà Ọlọ́run àwọn baba ńlá yín jà, torí ẹ ò ní ṣàṣeyọrí.”+
-
-
2 Kíróníkà 32:7, 8Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
7 “Ẹ jẹ́ onígboyà àti alágbára. Ẹ má bẹ̀rù, ẹ má sì jáyà nítorí ọba Ásíríà+ àti gbogbo ọ̀pọ̀ èèyàn tó wà pẹ̀lú rẹ̀, torí àwọn tó wà pẹ̀lú wa pọ̀ ju àwọn tó wà pẹ̀lú rẹ̀.+ 8 Agbára èèyàn ló gbẹ́kẹ̀ lé,* àmọ́ Jèhófà Ọlọ́run wa ló wà pẹ̀lú wa láti ràn wá lọ́wọ́, kó sì jà fún wa.”+ Ọ̀rọ̀ Hẹsikáyà ọba Júdà sì fún àwọn èèyàn náà lókun.+
-