-
1 Àwọn Ọba 7:23-26Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
23 Lẹ́yìn náà, ó fi irin ṣe Òkun.*+ Ó rí ribiti, fífẹ̀ ẹnu rẹ̀ jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ mẹ́wàá, gíga rẹ̀ jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ márùn-ún, okùn ìdíwọ̀n ọgbọ̀n (30) ìgbọ̀nwọ́ ló sì lè yí i ká.*+ 24 Àwọn iṣẹ́ ọnà tó rí bí akèrègbè+ wà nísàlẹ̀ ẹnu rẹ̀ yí ká, mẹ́wàá nínú ìgbọ̀nwọ́ kan, wọ́n yí Òkun náà po, ìlà méjì àwọn iṣẹ́ ọnà tó rí bí akèrègbè náà ni ó ṣe mọ́ ọn lára. 25 Wọ́n gbé Òkun náà ka orí akọ màlúù méjìlá (12),+ mẹ́ta dojú kọ àríwá, mẹ́ta dojú kọ ìwọ̀ oòrùn, mẹ́ta dojú kọ gúúsù, mẹ́ta sì dojú kọ ìlà oòrùn; Òkun náà wà lórí wọn, gbogbo wọn sì kọ̀dí sí abẹ́ Òkun náà. 26 Ìnípọn rẹ̀ jẹ́ ìbú ọwọ́ kan;* ẹnu rẹ̀ sì dà bí ẹnu ife, bí ìtànná òdòdó lílì. Ẹgbẹ̀rún méjì (2,000) báàtì* ni ó ń gbà.
-