-
2 Àwọn Ọba 9:17Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
17 Bí olùṣọ́ ṣe dúró sórí ilé gogoro tó wà ní Jésírẹ́lì, ó rí ọ̀gọ̀ọ̀rọ̀ àwọn ọkùnrin Jéhù tí wọ́n ń bọ̀. Ní kíá, ó sọ pé: “Mo rí ọ̀pọ̀ èèyàn tó ń bọ̀.” Jèhórámù bá sọ pé: “Mú agẹṣinjagun kan, kí o rán an lọ pàdé wọn, kó sì béèrè pé, ‘Ṣé àlàáfíà lẹ bá wá?’”
-
-
2 Kíróníkà 26:9, 10Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
9 Yàtọ̀ síyẹn, Ùsáyà kọ́ àwọn ilé gogoro+ sí Jerúsálẹ́mù lẹ́gbẹ̀ẹ́ Ẹnubodè Igun+ àti lẹ́gbẹ̀ẹ́ Ẹnubodè Àfonífojì+ àti lẹ́gbẹ̀ẹ́ Ìtì Ògiri, ó sì mú kí wọ́n lágbára. 10 Ó tún kọ́ àwọn ilé gogoro+ sí aginjù, ó sì gbẹ́ kòtò omi púpọ̀* (nítorí ó ní ẹran ọ̀sìn tó pọ̀ gan-an); ó ṣe bákan náà ní Ṣẹ́fẹ́là àti ní pẹ̀tẹ́lẹ̀.* Ó ní àwọn àgbẹ̀ àti àwọn tó ń rẹ́wọ́ àjàrà ní àwọn òkè àti ní Kámẹ́lì, nítorí ó fẹ́ràn iṣẹ́ àgbẹ̀.
-