-
1 Kíróníkà 15:16, 17Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
16 Dáfídì wá sọ fún àwọn olórí ọmọ Léfì pé kí wọ́n yan àwọn arákùnrin wọn tó jẹ́ akọrin láti máa fi ayọ̀ kọrin, kí wọ́n máa lo àwọn ohun ìkọrin, ìyẹn àwọn ohun ìkọrin olókùn tín-ín-rín àti háàpù+ pẹ̀lú síńbálì.*+
17 Torí náà, àwọn ọmọ Léfì yan Hémánì+ ọmọ Jóẹ́lì, lára àwọn arákùnrin rẹ̀, wọ́n yan Ásáfù+ ọmọ Berekáyà, lára àwọn ọmọ Mérárì tí wọ́n jẹ́ arákùnrin wọn, wọ́n yan Étánì+ ọmọ Kuṣáyà.
-
-
1 Kíróníkà 25:1, 2Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
25 Síwájú sí i, Dáfídì àti àwọn olórí àwùjọ àwọn tó ń ṣiṣẹ́ ìsìn ya àwọn kan lára àwọn ọmọ Ásáfù, Hémánì àti Jédútúnì+ sọ́tọ̀ láti máa fi háàpù, àwọn ohun ìkọrin olókùn tín-ín-rín+ àti síńbálì*+ sọ tẹ́lẹ̀. Orúkọ àwọn tó ń ṣe iṣẹ́ ìsìn yìí ni, 2 látinú àwọn ọmọ Ásáfù: Sákúrì, Jósẹ́fù, Netanáyà àti Áṣárélà, àwọn ọmọ Ásáfù lábẹ́ ìdarí Ásáfù, ẹni tó ń sọ tẹ́lẹ̀ lábẹ́ àṣẹ ọba.
-