ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • 2 Kíróníkà 36:15, 16
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 15 Jèhófà Ọlọ́run àwọn baba ńlá wọn ń kìlọ̀ fún wọn nípasẹ̀ àwọn òjíṣẹ́ rẹ̀, ó ń kìlọ̀ fún wọn léraléra, nítorí pé àánú àwọn èèyàn rẹ̀ àti ibùgbé rẹ̀ ń ṣe é. 16 Ṣùgbọ́n wọ́n ń fi àwọn òjíṣẹ́ Ọlọ́run tòótọ́ ṣẹ̀sín,+ wọn ò ka ọ̀rọ̀ rẹ̀ sí,+ wọ́n sì ń fi àwọn wòlíì rẹ̀ ṣe yẹ̀yẹ́,+ títí ìbínú Jèhófà fi ru sí àwọn èèyàn rẹ̀,+ tí ọ̀rọ̀ wọn sì kọjá àtúnṣe.

  • Àìsáyà 42:24
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 24 Ta ló ti mú kí wọ́n kó ohun ìní Jékọ́bù,

      Tó sì mú kí wọ́n kó ẹrù Ísírẹ́lì?

      Ṣebí Jèhófà ni, Ẹni tí a ṣẹ̀?

      Wọ́n kọ̀ láti rìn ní àwọn ọ̀nà Rẹ̀,

      Wọn ò sì ṣègbọràn sí òfin* Rẹ̀.+

  • Jeremáyà 40:2, 3
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 2 Ìgbà náà ni olórí ẹ̀ṣọ́ mú Jeremáyà, ó sì sọ fún un pé: “Jèhófà Ọlọ́run rẹ ló sọ pé àjálù yìí máa bá ibí yìí, 3 Jèhófà sì ti mú kó ṣẹlẹ̀ bó ṣe sọ, nítorí pé ẹ̀yin èèyàn yìí ti ṣẹ Jèhófà, ẹ kò sì ṣègbọràn sí ohùn rẹ̀. Ìdí nìyẹn tí èyí fi ṣẹlẹ̀ sí yín.+

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́