-
Ẹ́kísódù 23:10, 11Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
10 “Ọdún mẹ́fà ni kí o fi fún irúgbìn sí ilẹ̀ rẹ, kí o sì fi kórè èso rẹ̀.+ 11 Àmọ́ ní ọdún keje, kí o fi ilẹ̀ náà sílẹ̀ láìro, má fi dá oko. Àwọn tó jẹ́ aláìní nínú àwọn èèyàn rẹ yóò jẹ nínú rẹ̀, àwọn ẹran inú igbó yóò sì jẹ ohun tí wọ́n bá ṣẹ́ kù. Ohun tí o máa ṣe sí ọgbà àjàrà rẹ àti àwọn igi ólífì rẹ nìyẹn.
-
-
Léfítíkù 25:4, 5Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
4 Àmọ́ kí ọdún keje jẹ́ sábáàtì fún ilẹ̀ náà, tí ẹ ò ní ṣiṣẹ́ kankan níbẹ̀, sábáàtì fún Jèhófà. Ẹ ò gbọ́dọ̀ fún irúgbìn sí oko yín tàbí kí ẹ rẹ́wọ́ àjàrà yín. 5 Ẹ ò gbọ́dọ̀ kórè ohun tó hù fúnra rẹ̀ látinú ọkà tó ṣẹ́ kù lẹ́yìn tí ẹ kórè, ẹ má sì kó àwọn èso àjàrà yín tí ẹ ò tíì rẹ́wọ́ rẹ̀ jọ. Ẹ jẹ́ kí ilẹ̀ náà sinmi pátápátá fún ọdún kan.
-