- 
	                        
            
            Ẹ́kísódù 9:23Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
- 
                            - 
                                        23 Mósè wá na ọ̀pá rẹ̀ sí ọ̀run, Jèhófà sì mú kí ààrá sán, yìnyín bọ́, iná* sọ̀ kalẹ̀, Jèhófà sì ń mú kí òjò yìnyín rọ̀ sórí ilẹ̀ Íjíbítì. 
 
- 
                                        
- 
	                        
            
            1 Sámúẹ́lì 12:17, 18Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
- 
                            - 
                                        17 Òní kọ́ ni ọjọ́ ìkórè àlìkámà* ni? Màá ké pe Jèhófà kí ó sán ààrá kí ó sì rọ òjò; kí ẹ wá mọ̀, kí ẹ sì lóye pé ohun búburú ni ẹ ṣe lójú Jèhófà nígbà tí ẹ ní kí ó fún yín ní ọba.”+ 18 Ni Sámúẹ́lì bá ké pe Jèhófà, Jèhófà wá sán ààrá, ó sì rọ òjò ní ọjọ́ yẹn, tí gbogbo àwọn èèyàn náà fi bẹ̀rù Jèhófà àti Sámúẹ́lì gidigidi. 
 
-