ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Jẹ́nẹ́sísì 18:14
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 14 Ǹjẹ́ a rí ohun tó pọ̀ jù fún Jèhófà+ láti ṣe? Màá pa dà sọ́dọ̀ rẹ ní àkókò yìí lọ́dún tó ń bọ̀, Sérà yóò sì bí ọmọkùnrin kan.”

  • Sáàmù 135:6
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 6 Jèhófà ń ṣe gbogbo ohun tó bá fẹ́+

      Ní ọ̀run àti ní ayé, nínú òkun àti nínú gbogbo ibú omi.

  • Àìsáyà 43:13
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 13 Bákan náà, Ẹnì kan náà ni mí+ nígbà gbogbo;

      Kò sì sí ẹni tó lè já ohunkóhun gbà kúrò lọ́wọ́ mi.+

      Tí mo bá ń ṣe nǹkan kan, ta ló lè dá mi dúró?”+

  • Àìsáyà 55:10, 11
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 10 Torí bí òjò àti yìnyín ṣe ń rọ̀ láti ọ̀run gẹ́lẹ́,

      Tí kì í sì í pa dà síbẹ̀, àfi tó bá mú kí ilẹ̀ rin, tó jẹ́ kó méso jáde, kí nǹkan sì hù,

      Tó jẹ́ kí ẹni tó fúnrúgbìn ká irúgbìn, tí ẹni tó ń jẹun sì rí oúnjẹ,

      11 Bẹ́ẹ̀ ni ọ̀rọ̀ mi tó ti ẹnu mi jáde máa rí.*+

      Kò ní pa dà sọ́dọ̀ mi láìṣẹ,+

      Àmọ́ ó dájú pé ó máa ṣe ohunkóhun tí inú mi bá dùn sí,*+

      Ó sì dájú pé ohun tí mo rán an pé kó ṣe máa yọrí sí rere.

  • Jeremáyà 32:17
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 17 “Áà, Jèhófà Olúwa Ọba Aláṣẹ! Wò ó! Agbára ńlá rẹ+ àti apá rẹ tí o nà jáde lo fi dá ọ̀run àti ayé. Kò sí ohun tó ṣòroó ṣe fún ọ,

  • Máàkù 10:27
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 27 Jésù wò wọ́n tààrà, ó sì sọ pé: “Lójú èèyàn, kò ṣeé ṣe, àmọ́ kò rí bẹ́ẹ̀ lójú Ọlọ́run, torí ohun gbogbo ṣeé ṣe fún Ọlọ́run.”+

  • Lúùkù 18:27
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 27 Ó sọ pé: “Àwọn ohun tí kò ṣeé ṣe fún èèyàn ṣeé ṣe fún Ọlọ́run.”+

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́