ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Jẹ́nẹ́sísì 4:9, 10
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 9 Lẹ́yìn náà, Jèhófà bi Kéènì pé: “Ibo ni Ébẹ́lì arákùnrin rẹ wà?” Ó fèsì pé: “Mi ò mọ̀. Ṣé èmi ni olùṣọ́ arákùnrin mi ni?” 10 Ọlọ́run wá sọ pé: “Kí lo ṣe yìí? Tẹ́tí kó o gbọ́ mi! Ẹ̀jẹ̀ àbúrò rẹ ń ké jáde sí mi láti inú ilẹ̀.+

  • Jẹ́nẹ́sísì 9:5
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 5 Yàtọ̀ sí ìyẹn, èmi yóò béèrè ẹ̀jẹ̀ yín tó jẹ́ ẹ̀mí yín* pa dà. Èmi yóò béèrè lọ́wọ́ gbogbo ohun alààyè; ọwọ́ kálukú ni màá sì ti béèrè ẹ̀mí arákùnrin rẹ̀.+

  • Diutarónómì 32:43
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    •  43 Ẹ bá àwọn èèyàn+ rẹ̀ yọ̀, ẹ̀yin orílẹ̀-èdè,

      Torí ó máa gbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ àwọn ìránṣẹ́+ rẹ̀,

      Ó máa san àwọn ọ̀tá+ rẹ̀ lẹ́san,

      Ó sì máa ṣe ètùtù fún ilẹ̀ àwọn èèyàn rẹ̀.”*

  • 2 Àwọn Ọba 9:24
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 24 Jéhù mú ọfà,* ó sì ta á lu Jèhórámù ní àárín méjì ẹ̀yìn rẹ̀, ọfà náà jáde ní ọkàn rẹ̀, ó sì ṣubú sínú kẹ̀kẹ́ ogun rẹ̀.

  • 2 Àwọn Ọba 9:26
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 26 ‘“Bí mo ṣe rí ẹ̀jẹ̀ Nábótì+ àti ẹ̀jẹ̀ àwọn ọmọ rẹ̀ lánàá,” ni Jèhófà wí, “màá san án pa dà+ fún ọ ní ilẹ̀ yìí kan náà,” ni Jèhófà wí.’ Torí náà, gbé e, kí o sì jù ú sórí ilẹ̀ náà gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ tí Jèhófà sọ.”+

  • 2 Àwọn Ọba 24:3, 4
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 3 Ó dájú pé àṣẹ tí Jèhófà pa ló mú kí èyí ṣẹlẹ̀ sí Júdà, kí ó lè mú wọn kúrò níwájú rẹ̀+ nítorí gbogbo àwọn ẹ̀ṣẹ̀ tí Mánásè dá+ 4 àti nítorí ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ tí ó ta sílẹ̀,+ torí ó ti fi ẹ̀jẹ̀ àwọn aláìṣẹ̀ kún Jerúsálẹ́mù, Jèhófà kò sì fẹ́ dárí jì wọ́n.+

  • Lúùkù 11:49-51
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 49 Ìdí nìyẹn tí ọgbọ́n Ọlọ́run náà fi sọ pé: ‘Màá rán àwọn wòlíì àti àwọn àpọ́sítélì sí wọn, wọ́n máa pa àwọn kan, wọ́n sì máa ṣe inúnibíni sí àwọn kan lára wọn, 50 ká lè di ẹ̀bi ẹ̀jẹ̀ gbogbo àwọn wòlíì tí wọ́n ta sílẹ̀ látìgbà ìpìlẹ̀ ayé ru* ìran yìí,+ 51 látorí ẹ̀jẹ̀ Ébẹ́lì+ títí dórí ẹ̀jẹ̀ Sekaráyà, tí wọ́n pa láàárín pẹpẹ àti ilé.’*+ Àní, mò ń sọ fún yín, a máa di ẹ̀bi rẹ̀ ru* ìran yìí.

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́