ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Lúùkù 4:17-21
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 17 Torí náà, wọ́n fún un ní àkájọ ìwé wòlíì Àìsáyà, ó ṣí àkájọ ìwé náà, ó sì rí ibi tí wọ́n kọ ọ́ sí pé: 18 “Ẹ̀mí Jèhófà* wà lára mi, torí ó ti yàn mí kí n lè kéde ìhìn rere fún àwọn aláìní. Ó rán mi láti kéde òmìnira fún àwọn ẹrú, pé àwọn afọ́jú máa pa dà ríran, láti mú kí àwọn tí wọ́n tẹ̀ rẹ́ máa lọ lómìnira,+ 19 láti wàásù ọdún ìtẹ́wọ́gbà Jèhófà.”*+ 20 Ló bá ká àkájọ ìwé náà, ó dá a pa dà fún ìránṣẹ́, ó sì jókòó; gbogbo àwọn tó wà nínú sínágọ́gù sì tẹjú mọ́ ọn. 21 Ó wá bẹ̀rẹ̀ sí í sọ fún wọn pé: “Òní ni ìwé mímọ́ tí ẹ ṣẹ̀ṣẹ̀ gbọ́ yìí ṣẹ.”+

  • Lúùkù 7:22
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 22 Ó dá wọn lóhùn pé: “Ẹ lọ ròyìn ohun tí ẹ ti rí, tí ẹ sì ti gbọ́ fún Jòhánù: Àwọn afọ́jú ti ń ríran báyìí,+ àwọn arọ ń rìn, à ń wẹ àwọn adẹ́tẹ̀ mọ́, àwọn adití ń gbọ́ràn,+ à ń jí àwọn òkú dìde, a sì ń sọ ìhìn rere fún àwọn aláìní.+

  • Ìṣe 26:17, 18
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 17 Màá sì gbà ọ́ lọ́wọ́ àwọn èèyàn yìí àti lọ́wọ́ àwọn orílẹ̀-èdè tí màá rán ọ sí+ 18 láti la ojú wọn,+ láti mú wọn kúrò nínú òkùnkùn+ wá sínú ìmọ́lẹ̀+ àti láti mú wọn kúrò lábẹ́ àṣẹ Sátánì+ wá sọ́dọ̀ Ọlọ́run, kí wọ́n lè rí ìdáríjì ẹ̀ṣẹ̀ gbà,+ kí wọ́n sì rí ogún láàárín àwọn tí ìgbàgbọ́ wọn nínú mi ti sọ wọ́n di mímọ́.’

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́