-
Àìsáyà 20:3, 4Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
3 Jèhófà wá sọ pé: “Bí ìránṣẹ́ mi Àìsáyà ṣe rìn káàkiri ní ìhòòhò, láìwọ bàtà fún ọdún mẹ́ta, láti fi ṣe àmì+ àti àpẹẹrẹ ohun tó máa ṣẹlẹ̀ sí Íjíbítì+ àti Etiópíà,+ 4 bẹ́ẹ̀ gẹ́lẹ́ ni ọba Ásíríà máa kó àwọn ẹrú Íjíbítì+ àti Etiópíà lọ sí ìgbèkùn, àwọn ọmọdékùnrin àtàwọn àgbà ọkùnrin, ní ìhòòhò àti láìwọ bàtà, ìdí wọn á sì hàn síta, Íjíbítì máa rin ìhòòhò.*
-
-
Ìsíkíẹ́lì 30:4Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
4 Idà yóò dojú kọ Íjíbítì, ìbẹ̀rù á sì bo Etiópíà nígbà tí òkú bá sùn ní Íjíbítì;
Wọ́n ti kó ọrọ̀ rẹ̀, wọ́n sì ti wó ìpìlẹ̀ rẹ̀.+
-