-
Jẹ́nẹ́sísì 7:15, 16Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
15 Wọ́n ń wọlé lọ bá Nóà nínú áàkì, ní méjì-méjì, lára onírúurú ẹran tó ní ẹ̀mí.* 16 Wọ́n wá wọlé, akọ àti abo nínú onírúurú ẹran, bí Ọlọ́run ṣe pàṣẹ fún un. Lẹ́yìn náà, Jèhófà ti ilẹ̀kùn pa.
-
-
Ẹ́kísódù 12:22, 23Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
22 Kí ẹ wá ki ìdìpọ̀ ewéko hísópù bọnú ẹ̀jẹ̀ tó wà nínú bàsíà, kí ẹ sì wọ́n ọn sí apá òkè ẹnu ọ̀nà àti sára òpó méjèèjì ilẹ̀kùn náà; kí ẹnì kankan nínú yín má sì jáde ní ẹnu ọ̀nà ilé rẹ̀ títí di àárọ̀. 23 Tí Jèhófà bá wá kọjá kó lè fi ìyọnu kọ lu àwọn ará Íjíbítì, tó sì rí ẹ̀jẹ̀ náà ní apá òkè ẹnu ọ̀nà àti lára òpó rẹ̀ méjèèjì, ó dájú pé Jèhófà yóò ré ẹnu ọ̀nà náà kọjá, kò sì ní jẹ́ kí ìyọnu ikú* wọnú ilé yín.+
-