27 “‘“Ṣùgbọ́n bí ẹ kò bá ṣègbọràn sí àṣẹ tí mo pa pé kí ẹ jẹ́ kí ọjọ́ Sábáàtì máa jẹ́ mímọ́, tí ẹ̀ ń ru ẹrù, tí ẹ sì ń gbé e gba àwọn ẹnubodè Jerúsálẹ́mù ní ọjọ́ Sábáàtì, ṣe ni màá sọ iná sí àwọn ẹnubodè rẹ̀, ó sì dájú pé á jó àwọn ilé gogoro tó láàbò ní Jerúsálẹ́mù run,+ a kò sì ní pa iná náà.”’”+