64 “Jèhófà máa tú ọ ká sáàárín gbogbo orílẹ̀-èdè, láti ìkángun kan ayé dé ìkángun kejì ayé,+ o sì máa ní láti sin àwọn ọlọ́run tí wọ́n fi igi àti òkúta ṣe níbẹ̀, àwọn ọlọ́run tí ìwọ àtàwọn baba ńlá rẹ kò mọ̀.+
18 “‘Màá fi idà,+ ìyàn àti àjàkálẹ̀ àrùn lé wọn, màá sọ wọ́n di ohun àríbẹ̀rù lójú gbogbo ìjọba ayé,+ màá sì sọ wọ́n di ẹni ègún àti ohun ìyàlẹ́nu, ohun àrísúfèé+ àti ẹni ẹ̀gàn láàárín gbogbo orílẹ̀-èdè tí màá fọ́n wọn ká sí,+