-
Mátíù 2:16-18Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
16 Nígbà tí Hẹ́rọ́dù rí i pé àwọn awòràwọ̀ náà ti já ọgbọ́n òun, inú bí i gidigidi, ó ránṣẹ́, ó sì ní kí wọ́n pa gbogbo ọmọkùnrin ní Bẹ́tílẹ́hẹ́mù àti ní gbogbo agbègbè rẹ̀, láti ọmọ ọdún méjì sí ìsàlẹ̀, gẹ́gẹ́ bí àkókò tó fara balẹ̀ wádìí lọ́wọ́ àwọn awòràwọ̀ náà.+ 17 Ohun tí a sọ nípasẹ̀ wòlíì Jeremáyà wá ṣẹ, pé: 18 “A gbọ́ ohùn kan ní Rámà, ẹkún àti ìpohùnréré ẹkún púpọ̀. Réṣẹ́lì+ ló ń sunkún torí àwọn ọmọ rẹ̀, kò sì fẹ́ kí wọ́n tu òun nínú, torí pé wọn kò sí mọ́.”+
-