-
Dáníẹ́lì 3:26, 27Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
26 Nebukadinésárì wá sún mọ́ ilẹ̀kùn iná ìléru tó ń jó náà, ó sì sọ pé: “Ṣádírákì, Méṣákì àti Àbẹ́dínígò, ẹ̀yin ìránṣẹ́ Ọlọ́run Gíga Jù Lọ,+ ẹ jáde, kí ẹ sì máa bọ̀!” Ṣádírákì, Méṣákì àti Àbẹ́dínígò sì jáde láti àárín iná náà. 27 Àwọn baálẹ̀, àwọn aṣíwájú, àwọn gómìnà àti àwọn ìjòyè ọba tí wọ́n pé jọ síbẹ̀+ rí i pé iná náà ò pa àwọn ọkùnrin yìí lára* rárá;+ iná ò ra ẹyọ kan lára irun orí wọn, aṣọ ìlékè wọn ò yí pa dà, wọn ò tiẹ̀ gbóòórùn iná lára wọn.
-