11 Ni Dáfídì bá di ẹ̀wù ara rẹ̀ mú, ó sì fà á ya, gbogbo àwọn ọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ náà sì ṣe bẹ́ẹ̀. 12 Wọ́n pohùn réré ẹkún, wọ́n sunkún, wọ́n sì gbààwẹ̀+ títí di ìrọ̀lẹ́ nítorí Sọ́ọ̀lù àti Jónátánì ọmọ rẹ̀ àti nítorí àwọn èèyàn Jèhófà àti ilé Ísírẹ́lì+ torí pé wọ́n ti fi idà pa wọ́n.