22 Baba mi ti fa ohun gbogbo lé mi lọ́wọ́, kò sẹ́ni tó mọ ẹni tí Ọmọ jẹ́, àfi Baba, kò sì sẹ́ni tó mọ ẹni tí Baba jẹ́, àfi Ọmọ+ àti ẹnikẹ́ni tí Ọmọ bá fẹ́ ṣí i payá fún.”+
20 Ṣùgbọ́n a mọ̀ pé Ọmọ Ọlọ́run ti wá,+ ó sì ti jẹ́ ká ní òye* ká lè mọ ẹni tòótọ́ náà. A sì wà ní ìṣọ̀kan pẹ̀lú ẹni tòótọ́ náà,+ nípasẹ̀ Jésù Kristi Ọmọ rẹ̀. Èyí ni Ọlọ́run tòótọ́ náà àti ìyè àìnípẹ̀kun.+