ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Mátíù 17:20
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 20 Ó sọ fún wọn pé: “Torí ìgbàgbọ́ yín kéré ni. Lóòótọ́ ni mo sọ fún yín, tí ẹ bá ní ìgbàgbọ́ tó rí bíi hóró músítádì, ẹ máa sọ fún òkè yìí pé, ‘Kúrò níbí lọ sí ọ̀hún,’ ó sì máa lọ, kò sì sí ohun tí ẹ ò ní lè ṣe.”+

  • Máàkù 11:23
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 23 Lóòótọ́ ni mo sọ fún yín pé ẹnikẹ́ni tó bá sọ fún òkè yìí pé, ‘Dìde, wọnú òkun,’ tí kò sì ṣiyèméjì nínú ọkàn rẹ̀, àmọ́ tó ní ìgbàgbọ́ pé ohun tí òun sọ máa rí bẹ́ẹ̀, ó máa rí bẹ́ẹ̀ fún un.+

  • Lúùkù 17:6
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 6 Olúwa wá sọ pé: “Tí ẹ bá ní ìgbàgbọ́ tó rí bíi hóró músítádì, ẹ máa sọ fún igi mọ́líbẹ́rì dúdú yìí pé, ‘Fà tu, kí o sì lọ fìdí sọlẹ̀ sínú òkun!’ ó sì máa gbọ́ tiyín.+

  • Jòhánù 11:40
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 40 Jésù sọ fún un pé: “Ṣebí mo sọ fún ọ pé tí o bá gbà gbọ́, o máa rí ògo Ọlọ́run?”+

  • Ìṣe 14:9, 10
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 9 Ọkùnrin yìí ń fetí sí Pọ́ọ̀lù bó ṣe ń sọ̀rọ̀. Bí Pọ́ọ̀lù ṣe tẹjú mọ́ ọn, tó sì rí i pé ó ní ìgbàgbọ́ pé òun lè rí ìwòsàn,+ 10 ó gbóhùn sókè pé: “Dìde lórí ẹsẹ̀ rẹ.” Ọkùnrin náà fò sókè, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í rìn.+

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́