-
Mátíù 26:18, 19Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
18 Ó dáhùn pé: “Ẹ lọ sínú ìlú, kí ẹ lọ bá Lágbájá, kí ẹ sì sọ fún un pé, ‘Olùkọ́ sọ pé: “Àkókò tí a yàn fún mi ti sún mọ́lé; èmi àti àwọn ọmọ ẹ̀yìn mi máa ṣe ayẹyẹ Ìrékọjá ní ilé rẹ.”’” 19 Torí náà, àwọn ọmọ ẹ̀yìn ṣe ohun tí Jésù sọ fún wọn gẹ́lẹ́, wọ́n sì múra sílẹ̀ fún Ìrékọjá.
-
-
Máàkù 14:13-16Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
13 Ó wá rán méjì lára àwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀, ó sọ fún wọn pé: “Ẹ lọ sínú ìlú, ọkùnrin kan tó ru ìṣà omi máa pàdé yín. Ẹ tẹ̀ lé e,+ 14 ibikíbi tó bá wọlé sí, ẹ sọ fún baálé ilé náà pé, ‘Olùkọ́ sọ pé: “Ibo ni yàrá àlejò wà, tí èmi àti àwọn ọmọ ẹ̀yìn mi ti lè jẹ Ìrékọjá?”’ 15 Ó sì máa fi yàrá ńlá kan hàn yín lókè, tó ti ní àwọn ohun tí a nílò, tó sì ti wà ní sẹpẹ́. Ẹ ṣètò rẹ̀ síbẹ̀ fún wa.” 16 Torí náà, àwọn ọmọ ẹ̀yìn náà jáde lọ, wọ́n sì wọnú ìlú náà, wọ́n rí i bó ṣe sọ fún wọn gẹ́lẹ́, wọ́n sì múra sílẹ̀ fún Ìrékọjá.
-