29 Jósẹ́fù múra kẹ̀kẹ́ ẹṣin rẹ̀ sílẹ̀, ó sì lọ pàdé Ísírẹ́lì bàbá rẹ̀ ní Góṣénì. Nígbà tó dé ọ̀dọ̀ rẹ̀, ó dì mọ́ ọn* lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀, ó sì sunkún fúngbà díẹ̀.*
5 Kí o kéde níwájú Jèhófà Ọlọ́run rẹ pé, ‘Ará Arémíà tó ń lọ káàkiri* ni bàbá mi,+ ó lọ sí Íjíbítì,+ ó sì di àjèjì tó ń gbé níbẹ̀, òun àti àwọn díẹ̀ tí wọ́n jẹ́ ará ilé rẹ̀.+ Àmọ́ ibẹ̀ ló ti di orílẹ̀-èdè ńlá, tó lágbára, tó sì pọ̀ rẹpẹtẹ.+