11 “Aláyọ̀ ni yín tí àwọn èèyàn bá pẹ̀gàn yín,+ tí wọ́n ṣe inúnibíni sí yín,+ tí wọ́n sì parọ́ oríṣiríṣi ohun burúkú mọ́ yín nítorí mi.+ 12 Ẹ máa yọ̀, kí inú yín sì dùn gidigidi,+ torí èrè yín+ pọ̀ ní ọ̀run, torí bí wọ́n ṣe ṣe inúnibíni sí àwọn wòlíì tó wà ṣáájú yín nìyẹn.+