ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • scl ojú ìwé 96-97
  • Ìmúkúrò Nínú Ìjọ

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ìmúkúrò Nínú Ìjọ
  • Àwọn Ẹsẹ Bíbélì Tó Lè Ran Àwa Kristẹni Lọ́wọ́
Àwọn Ẹsẹ Bíbélì Tó Lè Ran Àwa Kristẹni Lọ́wọ́
scl ojú ìwé 96-97

Ìmúkúrò Nínú Ìjọ

Kí nìdí tó fi yẹ káwọn alàgbà máa dáàbò bo ìjọ lọ́wọ́ àwọn tó ń hùwà burúkú?

2Ti 2:16, 17; 2Pe 2:1, 2; Jud 3, 4

Báwo ni ìwà burúkú tí arákùnrin tàbí arábìnrin kan hù ṣe lè kó bá gbogbo ìjọ lápapọ̀?

1Kọ 5:1, 2, 5, 6

  • Àpẹẹrẹ inú Bíbélì:

    • Joṣ 7:1, 4-14, 20-26—Nígbà tí Ákánì àti ìdílé rẹ̀ hùwà burúkú, gbogbo orílẹ̀-èdè Ísírẹ́lì ló jìyà

    • Jon 1:1-16—Nígbà tí Jónà ò ṣe ohun tí Jèhófà ní kó ṣe, ó fi ẹ̀mí gbogbo àwọn tí wọ́n jọ wà nínú ọkọ̀ sínú ewu

Àwọn ìwà wo ló yẹ kẹ́nì kan sá fún tí kò bá fẹ́ kí wọ́n mú òun kúrò nínú ìjọ Kristẹni?

Ro 16:17, 18; 1Kọ 5:11; 1Ti 1:20; Tit 3:10, 11

Tún wo “Ìwà Tó Yẹ Kristẹni”

Kí ló yẹ ká ṣe fún Kristẹni kan tó ń bá a lọ láti máa dá ẹ̀ṣẹ̀ tó burú gan-an?

1Kọ 5:11-13

Tún wo 1Jo 3:4, 6

Táwọn alàgbà bá ń gbọ́ ẹjọ́ ẹnì kan tó dá ẹ̀ṣẹ̀ tó burú jáì, àwọn ìlànà Bíbélì wo ló yẹ kí wọ́n fi sọ́kàn?

Di 13:12-14; 17:2-4, 7; Mt 18:16; 2Kọ 13:1; 1Ti 5:19

Tún wo Owe 18:13; 1Ti 5:21

Kí nìdí tó fi máa ń pọn dandan pé kí wọ́n bá àwọn kan wí tàbí mú wọn kúrò nínú ìjọ, báwo nìyẹn sì ṣe máa ṣe ìjọ láǹfààní?

1Kọ 5:3-6; 1Ti 5:20

Kí ni Bíbélì sọ nípa bó ṣe yẹ ká máa ṣe sáwọn tí wọ́n mú kúrò nínú ìjọ?

Ro 16:17; 1Kọ 5:11, 13

Kí ló máa ṣẹlẹ̀ tí ẹni tí wọ́n mú kúrò nínú ìjọ bá ronú pìwà dà?

2Kọ 2:6, 7

Tún wo “Ìrònúpìwàdà”

Kí ni gbogbo wa lè ṣe kí ìjọ lè wà ní mímọ́?

Le 5:1; Heb 12:15, 16

Tún wo Di 13:6-11

Tẹ́rù bá tiẹ̀ ń ba ẹnì kan pé wọ́n lè mú òun kúrò nínú ìjọ, kí nìdí tí kò fi yẹ kẹ́ni náà bo ẹ̀ṣẹ̀ tó dá mọ́lẹ̀?

Sm 32:1-5; Owe 28:13; Jem 5:14, 15

Tún wo “Ẹ̀ṣẹ̀—Ó Yẹ Ká Jẹ́wọ́ Ẹ̀ṣẹ̀ Wa”

Tí wọn ò bá tiẹ̀ tí ì mú ẹnì kan tó ń hùwà tí kò bójú mu kúrò nínú ìjọ, kí nìdí tí kò fi yẹ ká máa ṣe wọléwọ̀de pẹ̀lú ẹni náà?

1Kọ 15:33; 2Tẹ 3:14; 2Ti 2:20, 21

Kí ni Kristẹni kan lè pinnu láti ṣe tí wọ́n bá lù ú ní jìbìtì tàbí bà á lórúkọ jẹ́, kí ló sì lè mú kó pinnu láti ṣe bẹ́ẹ̀?

Mt 18:15-17, 21, 22; Kol 3:12-14; 1Pe 4:8

Tí ẹnì kan bá ń hùwà tí kò bójú mu, kí nìdí tó fi ṣe pàtàkì káwọn tí òtítọ́ jinlẹ̀ nínú wọn ran ẹni náà lọ́wọ́?

Ga 6:1; Tit 2:3-5

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́