ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • scl ojú ìwé 11-14
  • Àdúrà

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Àdúrà
  • Àwọn Ẹsẹ Bíbélì Tó Lè Ran Àwa Kristẹni Lọ́wọ́
Àwọn Ẹsẹ Bíbélì Tó Lè Ran Àwa Kristẹni Lọ́wọ́
scl ojú ìwé 11-14

Àdúrà

Báwo la ṣe mọ̀ pé Jèhófà máa ń tẹ́tí sí àdúrà wa tó sì máa ń dáhùn?

Sm 65:2; 145:18; 1Jo 5:14

Tún wo Sm 66:19; Iṣe 10:31; Heb 5:7

  • Àpẹẹrẹ inú Bíbélì:

    • 1Ọb 18:36-38—Nígbà táwọn wòlíì Báálì ń ta ko Èlíjà lórí Òkè Kámẹ́lì, ó gbàdúrà sí Jèhófà nípa ọ̀rọ̀ náà, Jèhófà sì dá a lóhùn lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀

    • Mt 7:7-11—Jésù ní ká tẹra mọ́ àdúrà, ó sì fi dá wa lójú pé Jèhófà Bàbá wa onífẹ̀ẹ́ máa dá wa lóhùn

Ta lẹnì kan ṣoṣo tó yẹ káwa Kristẹni máa gbàdúrà sí?

Sm 5:1, 2; 69:13; Mt 6:9; Flp 4:6

Orúkọ ta ló yẹ ká fi máa gbàdúrà sí Ọlọ́run?

Jo 15:16; 16:23, 24

Àdúrà àwọn wo ni Jèhófà máa ń dáhùn?

Iṣe 10:34, 35; 1Pe 3:12; 1Jo 3:22; 5:14

Àdúrà àwọn wo ni Jèhófà kì í dáhùn?

Owe 15:29; 28:9; Ais 1:15; Mik 3:4; Jem 4:3; 1Pe 3:7

  • Àpẹẹrẹ inú Bíbélì:

    • Joṣ 24:9, 10—Jèhófà kò dáhùn àdúrà Báláámù torí pé ohun tó béèrè ò bá ìfẹ́ rẹ̀ mu

    • Ais 1:15-17—Jèhófà ò gbọ́ àdúrà àwọn èèyàn ẹ̀ torí pé wọ́n ti di alágàbàgebè, ẹ̀jẹ̀ sì kún ọwọ́ wọn

Kí la máa ń sọ níparí àdúrà, kí sì nìdí tá a fi ń sọ ọ́?

1Kr 16:36; Sm 41:13; 72:19; 89:52; 1Kọ 14:16

Ṣé Bíbélì sọ pé ó pọn dandan ká kúnlẹ̀, ká dúró tàbí ká wà nípò kan pàtó tá a bá ń gbàdúrà?

1Ọb 8:54; Mk 11:25; Lk 22:39, 41; Jo 11:41

Tún wo Jon 2:1

Táwa èèyàn Jèhófà bá kóra jọ láti jọ́sìn, àwọn nǹkan wo la lè sọ nínú àdúrà wa?

Iṣe 4:23, 24; 12:5

  • Àpẹẹrẹ inú Bíbélì:

    • 1Kr 29:10-19—Ọba Dáfídì gbàdúrà níwájú àwọn ọmọ Ísírẹ́lì nígbà tí wọ́n fi tinútinú ṣètìlẹyìn fún kíkọ́ tẹ́ńpìlì

    • Iṣe 1:12-14—Àwọn àpọ́sítélì, àwọn arákùnrin Jésù, Màríà ìyá Jésù àtàwọn obìnrin olóòótọ́ míì kóra jọ sí yàrá òkè ní Jerúsálẹ́mù, wọ́n sì ń gbàdúrà pa pọ̀

Tá a bá ń gbàdúrà, kí nìdí tí kò fi yẹ ká máa gbéraga tàbí ká máa pe àfíyèsí sí ara wa?

Mt 6:5; Lk 18:10-14

Kí nìdí tó fi yẹ ká máa gbàdúrà tá a bá fẹ́ jẹun?

Mt 14:19; Iṣe 27:35; 1Kọ 10:25, 26, 30, 31

Kí nìdí tó fi yẹ ká máa gbàdúrà nígbà gbogbo?

Ro 12:12; Ef 6:18; 1Tẹ 5:17; 1Pe 4:7

  • Àpẹẹrẹ inú Bíbélì:

    • Da 6:6-10—Wọ́n halẹ̀ mọ́ wòlíì Dáníẹ́lì pé wọ́n máa pa á, síbẹ̀ ó ń bá a lọ láti máa gbàdúrà sí Jèhófà nínú yàrá tó wà lórí òrùlé rẹ̀

    • Lk 18:1-8—Jésù sọ àpèjúwe kan nípa adájọ́ tí kò bẹ̀rù Ọlọ́run, tó pa dà gbọ́ ẹjọ́ obìnrin opó kan torí pé obìnrin náà ò yéé wá sọ́dọ̀ ẹ̀. Ó lo àpèjúwe náà láti kọ́ wa pé Jèhófà máa dáhùn àdúrà wa tá ò bá jẹ́ kó sú wa

Kí ló yẹ ká ṣe tá a bá fẹ́ kí Ọlọ́run dárí ẹ̀sẹ̀ wa jì wá?

2Kr 7:13, 14

  • Àpẹẹrẹ inú Bíbélì:

    • 2Ọb 22:11-13, 18-20—Jèhófà ṣàánú Ọba Jòsáyà, ó sì fi inúure hàn sí i torí pé ó rẹ ara rẹ̀ sílẹ̀, ó sì wá Jèhófà

    • 2Kr 33:10-13—Ọba Mánásè rẹ ara ẹ̀ sílẹ̀, ó sì bẹ Jèhófà pé kó dárí ji òun. Jèhófà dárí jì í, ó sì dá a pa dà sórí ìtẹ́

Tá a bá fẹ́ kí Jèhófà máa dárí jì wá, kí ló yẹ káwa náà máa ṣe?

Mt 6:14, 15; Mk 11:25; Lk 17:3, 4

Kí nìdí tó fi yẹ ká máa gbàdúrà pé kí ìfẹ́ Jèhófà ṣẹ?

Mt 6:10; Lk 22:41, 42

Kí nìdí tí ìgbàgbọ́ fi ṣe pàtàkì tá a bá ń gbàdúrà?

Mk 11:24; Heb 6:10; Jem 1:5-7

Àwọn nǹkan wo la lè sọ nínú àdúrà?

Bí orúkọ Ọlọ́run ṣe máa di mímọ́

Lk 11:2

Bí Ìjọba Ọlọ́run ṣe máa ṣàkóso ayé

Mt 6:10

Bí ìfẹ́ Jèhófà ṣe máa ṣẹ

Mt 6:10; 26:42

Kí Jèhófà pèsè àwọn nǹkan tá a nílò fún wa

Lk 11:3

Kí Jèhófà dárí ẹ̀ṣẹ̀ wa jì wá

Da 9:19; Lk 11:4

Kí Jèhófà gbà wá lọ́wọ́ ìdẹwò

Mt 6:13

Ká máa dúpẹ́

Ef 5:20; Flp 4:6; 1Tẹ 5:17, 18

Kí Jèhófà jẹ́ ká mọ ohun tó fẹ́, kó fún wa ní ọgbọ́n àti òye

Owe 2:3-6; Flp 1:9; Jem 1:5

Tún wo Sm 119:34

  • Àpẹẹrẹ inú Bíbélì:

    • 1Ọb 3:11, 12—Ọba Sólómọ́nì sọ pé kí Jèhófà fún òun ní ọgbọ́n, Jèhófà sì fún un lọ́gbọ́n tí kò láfiwé

Ní kí Jèhófà fún ẹ ní ẹ̀mí mímọ́

Lk 11:13; Iṣe 8:14, 15

Máa gbàdúrà fáwọn ará, títí kan àwọn tí wọ́n ń ṣenúnibíni sí

Iṣe 12:5; Ro 15:30, 31; Jem 5:16

Tún wo Kol 4:12; 2Ti 1:3

Máa yin Jèhófà

Sm 86:12; Ais 25:1; Da 2:23

  • Àpẹẹrẹ inú Bíbélì:

    • Lk 10:21—Jésù yin Jèhófà ní gbangba torí pé ó fún àwọn onírẹ̀lẹ̀ láǹfààní láti mọ òtítọ́

    • Ifi 4:9-11—Àwọn áńgẹ́lì máa ń fún Jèhófà ní ọlá àti ògo tó tọ́ sí i

Máa gbàdúrà nípa àwọn tó wà nípò àṣẹ kí wọ́n lè fún wa lómìnira láti máa sin Jèhófà ní fàlàlà, ká sì máa wàásù láìsí ìdíwọ́

Mt 5:44; 1Ti 2:1, 2

Tún wo Jer 29:7

Ṣé ó bọ́gbọ́n mu kéèyàn gbàdúrà nígbà tó ń ṣèrìbọmi?

Lk 3:21

Ṣé ó yẹ ká máa gbàdúrà fáwọn tó ń ṣàìsàn nípa tẹ̀mí?

Jem 5:14, 15

Kí nìdí táwọn ọkùnrin kì í fi í borí tí wọ́n bá ń gbàdúrà, kí sì nìdí táwọn obìnrin fi sábà máa ń bo orí tí wọ́n bá ń gbàdúrà?

1Kọ 11:2-16

Tá a bá tiẹ̀ ń gbàdúrà tó gùn tàbí tá à ń fi ìmọ̀lára tó lágbára hàn nínú àdúrà wa, kí lohun tó ṣe pàtàkì jù sí Jèhófà?

Ida 3:41; Mt 6:7

  • Àpẹẹrẹ inú Bíbélì:

    • 1Ọb 18:25-29, 36-39—Nígbà tí wòlíì Èlíjà pe àwọn wòlíì Báálì níjà, léraléra làwọn wòlíì náà ń pe ọlọ́run wọn, àmọ́ kò dá wọn lóhùn

    • Iṣe 19:32-41—Nǹkan bíi wákàtí méjì làwọn abọ̀rìṣà tó wà nílùú Éfésù fi ń ké pe òrìṣà Átẹ́mísì, àmọ́ kò dá wọn lóhùn, ni akọ̀wé ìlú náà bá fẹ̀sùn kàn wọ́n pé wọ́n ń da ìlú rú

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́