ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • w94 2/1 ojú ìwé 32
  • Ẹsẹ Ìwé Mímọ́ Ojoojúmọ́ Fún Ọdún1994

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ẹsẹ Ìwé Mímọ́ Ojoojúmọ́ Fún Ọdún1994
  • Ilé-Ìṣọ́nà Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1994
Ilé-Ìṣọ́nà Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1994
w94 2/1 ojú ìwé 32

Ẹsẹ Ìwé Mímọ́ Ojoojúmọ́ Fún Ọdún1994

FEBRUARY

1. Kiyesi i, emi ó rán onṣẹ mi, yoo si tun ọ̀nà ṣe niwaju mi.​—Mal. 3:1. w-YR 12/1/92 3, 4a

2. Ẹ pa araayin mọ́ kuro ninu oriṣa.​—1 Joh. 5:21. w-YR 1/15/93 19, 20a

3. Nititori eyi mo fi awọn eékún mi kúnlẹ̀ fun Baba, ẹni ti olukuluku idile ní ọrun ati lori ilẹ̀-ayé jẹ ní gbèsè orukọ rẹ̀.​—Efe. 3:14, 15. w-YR 10/15/92 1, 2

4. Nitori ayọ ni ẹ o fi jade, alaafia ni a o fi tọ́ yin.​—Isa. 55:12. w-YR 9/15/92 3, 4

5. Ẹ lọ ki ẹ sì sọ awọn eniyan gbogbo orilẹ-ede di ọmọ-ẹ̀yìn, ki ẹ maa baptisi wọn ni orukọ Baba ati ti Ọmọkunrin, ati ti ẹmi mímọ́.​—Matt. 28:19. w-YR 9/1/92 2-5

6. Ẹ yin Jah, ẹyin eniyan! Ẹ fi iyin fun un, Oo ẹyin iranṣẹ Jehofa, ẹ yin orukọ Jehofa. Ǹjẹ́ ki orukọ Jehofa di abùkún-fún lati isinsinyi lọ àní titilọ gbére.​—Orin Da. 113:​1, 2, NW. w-YR 11/15/92 4, 5

7. Ọmọ mi, fiyesi ọgbọ́n mi, ki o si dẹti rẹ si oye mi. Lati maa pa ironu mọ́ ati ki ètè rẹ le pa imọ mọ́.​—Owe 5:​1, 2. w-YR 11/1/92 5, 6a

8. Ranti ẹlẹdaa rẹ nisinsinyi ni ọjọ ewe rẹ.​—Oniwasu 12:1. w-YR 1/1/93 13, 14

9. Nigba naa ni inu rẹ yoo dùn si ẹbọ ododo; pẹlu ọrẹ-ẹbọ sisun ati ọ̀tọ̀tọ̀ ọrẹ-ẹbọ sisun.​—Orin Da. 51:19. w-YR 3/15/93 20, 21a

10. Ẹ tẹriba, fun Ọlọrun.​—Jak. 4:7. w-YR 2/1/93 1, 2a

11. Ki ẹ si mu aṣibori igbala, ati idà ẹmi, ti i ṣe ọ̀rọ̀ Ọlọrun: Pẹlu gbogbo adura ati ẹbẹ ni ki ẹ maa gbadura nigba gbogbo ninu ẹmi, ki ẹ si maa ṣọra si i ninu iduroṣinṣin gbogbo, ati ẹ̀bẹ̀ fun gbogbo eniyan mímọ́.​—Efe. 6:​17, 18. w-YR 2/15/93 13a

12. Wọn ki yoo panilara, bẹẹni wọn ki yoo panirun ni gbogbo oke mímọ́ mi: nitori aye yoo kún fun imọ Oluwa gẹgẹ bi omi ti bo okun.​—Isa. 11:9. w-YR 10/1/92 17, 18a

13. Lati ila-oorun titi o fi de ìwọ̀ rẹ̀ orukọ Oluwa ni ki a yìn.​—Orin Da. 113:3. w-YR 11/15/92 6, 7

14. Bi awa ba mọọmọ dẹṣẹ lẹ̀yìn igba ti awa ba ti gba imọ otitọ kò tun si ẹbọ fun ẹṣẹ mọ́, bikoṣe ireti idajọ tí ó banilẹru.​—Heb. 10:​26, 27. w-YR 9/15/92 6

15. Èrò-inú wọn wà ninu okùnkùn, ti a si sọ wọn dàjèjì si ìyè tí ó jẹ ti Ọlọrun, nitori àìmọ̀kan ti ń bẹ ninu wọn, nitori àìmòye ọkàn-àyà wọn.​—Efe. 4:18, NW. w-YR 3/1/93 10, 11

16. Bẹẹ gẹgẹ ẹyin ọkọ, ẹ maa fi òye bá awọn aya yin gbé, ẹ maa fi ọlá fun aya, bi ohun eelo ti kò lagbara, . . . ki adura yin ki o ma baa ni idena.​—1 Pet. 3:7. w-YR 10/15/92 9, 10

17. Mo mọ̀ pe, oun o fi aṣẹ fun awọn ọmọ rẹ̀ ati fun awọn ara ile rẹ̀ lẹ́yìn rẹ̀, ki wọn ki o maa pa ọ̀nà OLUWA mọ́ lati ṣe ododo ati idajọ.—Gen. 18:19. w-YR 11/1/92 2-4

18. Bayii ni Ọlọrun Oluwa wi, ẹni tí ó dá ọrun, tí ó si nà wọn jade; ẹni tí ó tẹ́ aye, ati ohun tí ó ti inu rẹ̀ wá; ẹni tí ó fi èémí fun awọn eniyan lori rẹ̀, ati ẹmi fun awọn tí ó ń rin ninu rẹ̀.​—Isa. 42:5. w-YR 12/1/92 2, 3

19. A o si waasu ihinrere ijọba yii ni gbogbo aye.​—Matt. 24:14. w-YR 9/15/92 6-8b

20. Israeli, iwọ gbẹkẹle Oluwa: oun ni iranlọwọ wọn ati asà wọn. Ẹyin tí ó bẹru Oluwa, gbẹkẹle Oluwa: oun ni iranlọwọ wọn ati asà wọn.​—Orin Da 115:​9, 11. w-​YR 11/15/92 17

21. Oluwa! emi mọ pe, ọ̀nà eniyan kò si ni ipa araarẹ̀: kò si ni ipá eniyan ti ń rin lati tọ́ iṣisẹ rẹ̀.​—Jer. 10:23. w-YR 2/1/93 2, 3

22. Iwọ ti pèsè silẹ loju gbogbo eniyan, ìmọ́lẹ̀ kan fún mímú ìbòjú kuro loju awọn orilẹ-ede ati ògo awọn eniyan rẹ Israeli.​—Luku 2:​31, 32, NW. w-YR 1/15/93 4-6

23. Emi o yọ̀ gidigidi ninu Oluwa, ọkàn mi yoo yọ ninu Ọlọrun mi; nitori o ti fi [aṣọ ìgbàlà wọ mi, NW].​—Isa. 61:10. w-YR 1/1/93 2, 3

24. Mu ọkàn-aya mi ṣọ̀kan lati bẹ̀rù orukọ rẹ.​—Orin Da. 86:11, NW. w-YR 12/15/92 7a

25. Bi ẹnikẹni ninu yin láyé yii ba rò pe oun gbọ́n, ẹ jẹ ki o di aṣiwere, kí ó lè baà gbọ́n.​—1 Kor. 3:18. w-YR 9/15/92 16, 17b

26. Ta ni ki yoo bẹru, Oluwa, ti kì yoo si fi ogo fun orukọ rẹ? nitori iwọ nikanṣoṣo ni mímọ́: gbogbo awọn orilẹ-ede ni yoo si wá, ti yoo si foribalẹ niwaju rẹ̀; nitori a ti fi ìdájọ́ rẹ hàn.​—Ìfi. 15:4. w-YR 11/15/92 4-6b

27. Níwọ̀n bí wọ́n ti wá rékọja gbogbo agbára òye ìwàrere, wọ́n fi ara wọn fún ìwà àìníjàánu lati máa fi ìwà ìwọ̀ra hu onírúurú ìwà àìmọ̀ gbogbo.​—Efe. 4:19, NW. w-YR 3/1/93 16

28. Kiyesi i, ninu aiṣedeedee ni a gbé bí mi: ati ninu ẹ̀ṣẹ̀ ni ìyá mi sì lóyún mi.​—Orin Da. 51:5. w-YR 3/15/93 14, 15

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́