ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • w97 12/1 ojú ìwé 32
  • Òfin Mẹ́wàá

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Òfin Mẹ́wàá
  • Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1997
Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1997
w97 12/1 ojú ìwé 32

Òfin Mẹ́wàá

BÍṢỌ́Ọ̀BÙ Gloucester ti ilẹ̀ England ṣàwárí pé èyí tí ó ju ìdajì àwọn àlùfáà abẹ́ rẹ̀ ni kò lè ka Òfin Mẹ́wàá sórí, ìpín 10 nínú ọgọ́rùn-ún wọn kò sì mọ ibi tí ó wà nínú Bíbélì. Ṣùgbọ́n, nǹkan bí 450 ọdún sẹ́yìn ni ìyẹn. Ipò nǹkan ha ti sàn sí i láti ìgbà náà wá bí? Rárá o—gẹ́gẹ́ bí ìwádìí àṣekárí tí ìwé agbéròyìnjáde Sunday Times ṣe láàárín àwọn àlùfáà Áńgílíkà ti ṣí i payá.

Nínú gbogbo àlùfáà 200 tí a fọ̀rọ̀ wá lẹ́nu wò, kìkì ìpín 34 nínú ọgọ́rùn-ún ni ó lè ka gbogbo Òfin Mẹ́wàá náà sórí. Lára àwọn tí ó kù, ọ̀kan rò pé wọ́n ti le jù, òmíràn sì kà wọ́n sí òfin tí kò yanjú ìṣòro ìwà híhù òde òní.

Ìwọ ha mọ Òfin Mẹ́wàá náà tàbí ibi tí a ti lè rí wọn? A ṣàkọsílẹ̀ wọn sínú Ẹ́kísódù, ìwé kejì nínú Bíbélì, ní àwọn ẹsẹ 17 àkọ́kọ́ nínú orí 20. Èé ṣe tí o kò fi kà wọ́n? Ọ̀nà rírọrùn láti gbà pín wọn nìyí. Mẹ́rin àkọ́kọ́ ní í ṣe pẹ̀lú ìjọsìn wa sí Ọlọ́run, ìkarùn-ún tẹnu mọ́ ìgbésí ayé ìdílé, ìkẹfà sí ìkẹsàn-án ní í ṣe pẹ̀lú ipò ìbátan wa pẹ̀lú àwọn ènìyàn ẹlẹgbẹ́ wa, ìkẹwàá sì jẹ́ àrà ọ̀tọ̀, ó ń mú kí a ṣàwárí ohun tí ń bẹ nínú ọkàn wa fínnífínní, kí a gbé ìsúnniṣe wa yẹ̀ wò. Àkópọ̀ kúkúrú nípa bí àwọn Kristẹni ṣe lè lo àwọn ìlànà rẹ̀ nìyí.

Àkọ́kọ́: Fún Ẹlẹ́dàá wa ní ìfọkànsìn tí a yà sọ́tọ̀ gédégbé. Ìkejì: Má lo ère nínú ìjọsìn. Ìkẹta: Bọ̀wọ̀ fún orúkọ Ọlọ́run, kí o sì bọlá fún un nígbà gbogbo. Ìkẹrin: Wá àkókò láti pọkàn pọ̀ sórí àwọn ọ̀ràn tẹ̀mí, láìsí ìpínyà ọkàn. Ìkarùn-ún: Ẹ̀yin ọmọ, ẹ bọ̀wọ̀ fún àwọn òbí yín. Ìkẹfà: Má ṣe pànìyàn. Ìkeje: Yẹra fún panṣágà. Ìkẹjọ: Má jalè. Ìkẹsàn-án: Sọ òtítọ́. Ìkẹwàá: Yẹra fún ojúkòkòrò.

Òfin Mẹ́wàá jẹ́ ara àkójọ òfin tí a fún Mósè. Ṣùgbọ́n àwọn ìlànà inú wọn wà títí ayé. (Róòmù 6:14; Kólósè 2:13, 14) Fún ìdí yìí, àwọn ọmọlẹ́yìn Jésù fa ọ̀rọ̀ yọ láti inú Òfin Mẹ́wàá, wọ́n sì tọ́ka sí i. (Róòmù 13:8-10) Ẹ wo bí ìgbésí ayé ì bá ti láyọ̀ tó—tí ì bá sì ti wà láìséwu tó—lónìí, ká ní gbogbo ènìyàn bọ̀wọ̀ fún àwọn ìlànà tí Ọlọ́run mí sí wọ̀nyí, tí wọ́n sì gbé ní ìbámu pẹ̀lú wọn!

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́